Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 60:7-12 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase;Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi,Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.

8. Moabu ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi;lórí Edomu ni n óo bọ́ bàtà mi lé;n óo sì hó ìhó ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistia.”

9. Ta ni yóo mú mi wọ inú ìlú olódi náà?Ta ni yóo mú mi lọ sí Edomu?

10. Ọlọrun, o kò ha ti kọ̀ wá sílẹ̀?Ọlọrun, o ò bá àwọn ọmọ ogun wa jáde lọ sójú ogun mọ́.

11. Ràn wá lọ́wọ́, bá wa gbógun ti àwọn ọ̀tá wa,nítorí pé asán ni ìrànlọ́wọ́ eniyan.

12. Pẹlu àtìlẹ́yìn Ọlọrun a óo ṣe akin,nítorí òun ni yóo tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 60