4. O ti ta àsíá ogun fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,kí wọ́n baà lè rí ààbò lọ́wọ́ ọfà ọ̀tá.
5. Kí á lè gba àyànfẹ́ rẹ là,fi ọwọ́ agbára rẹ ṣẹgun fún wa,kí o sì dá wa lóhùn.
6. Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀,ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu,n óo sì pín àfonífojì Sukotu.
7. Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase;Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi,Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.