Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 59:4-9 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Láìjẹ́ pé mo ṣẹ̀, wọ́n ń sáré kiri, wọ́n múra dè mí.Paradà, wá ràn mí lọ́wọ́, kí o sì rí i fúnra rẹ.

5. Ìwọ, OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun,Ọlọrun Israẹli,jí gìrì, kí o jẹ gbogbo orílẹ̀-èdè níyà;má da ẹnìkan kan sí ninu àwọn tí ń fi ìwà ọ̀dàlẹ̀ pète ibi.

6. Ní alaalẹ́, wọn á pada wá,wọn á máa hu bí ajá, wọn a sì máa kiri ìlú.

7. Ẹ gbọ́ ohun tí wọn ń sọ jáde lẹ́nu,ẹ wo ahọ́n wọn bí idà;wọ́n sì ń wí ninu ara wọn pé, “Ta ni yóo gbọ́ ohun tí à ń sọ?”

8. Ṣugbọn ìwọ OLUWA ń fi wọ́n rẹ́rìn-ín,o sì ń fi gbogbo orílẹ̀-èdè ṣe yẹ̀yẹ́.

9. Ọlọrun, agbára mi, ojú rẹ ni mò ń wò,nítorí ìwọ, Ọlọrun, ni odi mi.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 59