Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 51:11-19 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Má ta mí nù kúrò lọ́dọ̀ rẹ,má sì gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.

12. Dá ayọ̀ ìgbàlà rẹ pada fún mi,kí o sì fi ẹ̀mí àtiṣe ìfẹ́ rẹ gbé mi ró.

13. Nígbà náà ni n óo máa kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ọ̀nà rẹ,àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóo sì máa yipada sí ọ.

14. Gbà mí lọ́wọ́ ẹ̀bi ìpànìyàn, Ọlọrun,ìwọ Ọlọrun, Olùgbàlà mi,n óo sì máa fi orin kéde iṣẹ́ rere rẹ.

15. OLUWA, là mí ní ohùn,n óo sì máa ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ.

16. Bí ó bá jẹ́ pé o fẹ́ ẹbọ ni, ǹ bá mú wá fún ọ;ṣugbọn o ò tilẹ̀ fẹ́ ẹbọ sísun.

17. Ẹbọ tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ ìwọ Ọlọrun ni ẹ̀mí ìròbìnújẹ́,ọkàn ìròbìnújẹ́ ati ìrònúpìwàdà ni ìwọ kì yóo gàn.

18. Jẹ́ kí ó dára fún Sioni ninu ìdùnnú rẹ;tún odi Jerusalẹmu mọ.

19. Nígbà náà ni inú rẹ yóo dùn sí ẹbọ tí ó tọ́,ẹbọ sísun, ati ẹbọ tí a sun lódidi;nígbà náà ni a óo fi akọ mààlúù rúbọ lórí pẹpẹ rẹ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 51