Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 51:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;nítorí ọ̀pọ̀ àánú rẹ pa ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.

2. Wẹ̀ mí mọ́ kúrò ninu àìdára mi,kí o sì wẹ̀ mí kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ mi!

3. Nítorí mo mọ ibi tí mo ti ṣẹ̀,nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi sì wà níwájú mi.

4. Ìwọ nìkan, àní, ìwọ nìkan ṣoṣo ni mo ṣẹ̀,tí mo ṣe ohun tí ó burú lójú rẹ,kí ẹjọ́ rẹ lè tọ́ nígbà tí o bá ń dájọ́,kí ọkàn rẹ lè mọ́ nígbà tí o bá ń ṣe ìdájọ́.

5. Dájúdájú, ninu àìdára ni a bí mi,ninu ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mi sì lóyún mi.

6. O fẹ́ràn òtítọ́ inú;nítorí náà, kọ́ mi lọ́gbọ́n ní kọ́lọ́fín ọkàn mi.

7. Fi ewé hisopu fọ̀ mí, n óo sì mọ́;wẹ̀ mí, n óo sì funfun ju ẹ̀gbọ̀n òwú lọ.

8. Fún mi ní ayọ̀ ati inú dídùn,kí gbogbo egungun mi tí ó ti rún lè máa yọ̀.

9. Mójú kúrò lára ẹ̀ṣẹ̀ mi,kí o sì pa gbogbo àìdára mi rẹ́.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 51