Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 50:5-14 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ó ní, “Ẹ kó àwọn olùfọkànsìn mi jọ sọ́dọ̀ mi,àwọn tí wọ́n ti fi ẹbọ bá mi dá majẹmu!”

6. Ojú ọ̀run ń kéde òdodo rẹ̀ péỌlọrun ni onídàájọ́.

7. “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin eniyan mi, n óo sọ̀rọ̀,Israẹli, n óo takò yín.Èmi ni Ọlọrun, Ọlọrun yín.

8. N kò ba yín wí nítorí ẹbọ rírú;nígbà gbogbo ni ẹ̀ ń rú ẹbọ sísun sí mi.

9. N kò ní gba akọ mààlúù lọ́wọ́ yín,tabi òbúkọ láti agbo ẹran yín.

10. Nítorí èmi ni mo ni gbogbo ẹran inú igbó,tèmi sì ni gbogbo mààlúù tó wà lórí ẹgbẹrun òkè.

11. Gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ni mo mọ̀,tèmi sì ni gbogbo nǹkan tí ń rìn ninu pápá.

12. “Bí ebi bá tilẹ̀ pa mí, ẹ̀yin kọ́ ni n óo sọ fún,nítorí èmi ni mo ni gbogbo ayé ati àwọn nǹkan tí ó wà ninu rẹ̀.

13. Ṣé èmi a máa jẹ ẹran akọ mààlúù?Àbí mà máa mu ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́?

14. Ọpẹ́ ni kí ẹ fi rúbọ sí Ọlọrun,kí ẹ sì máa san ẹ̀jẹ́ yín fún Ọ̀gá Ògo.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 50