1. OLUWA, Ọlọrun Alágbára ti sọ̀rọ̀:ó ké sí gbogbo ayéláti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn.
2. Ọlọrun yọ bí ọjọ́ láti Sioni,ìlú tó dára, tó lẹ́wà.
3. Ọlọrun wa ń bọ̀, kò dákẹ́:iná ajónirun ń jó níwájú rẹ̀;ìjì líle sì ń jà yí i ká.
4. Ó ké sí ọ̀run lókè;ó pe ayé pẹlu láti gbọ́ ìdájọ́ tí yóo ṣe fún àwọn eniyan rẹ̀.
5. Ó ní, “Ẹ kó àwọn olùfọkànsìn mi jọ sọ́dọ̀ mi,àwọn tí wọ́n ti fi ẹbọ bá mi dá majẹmu!”
6. Ojú ọ̀run ń kéde òdodo rẹ̀ péỌlọrun ni onídàájọ́.
7. “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin eniyan mi, n óo sọ̀rọ̀,Israẹli, n óo takò yín.Èmi ni Ọlọrun, Ọlọrun yín.
8. N kò ba yín wí nítorí ẹbọ rírú;nígbà gbogbo ni ẹ̀ ń rú ẹbọ sísun sí mi.
9. N kò ní gba akọ mààlúù lọ́wọ́ yín,tabi òbúkọ láti agbo ẹran yín.