Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 5:4-8 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọrun tí inú rẹ̀ dùn sí ìwà burúkú;àwọn ẹni ibi kò sì lè bá ọ gbé.

5. Àwọn tí ń fọ́nnu kò lè dúró níwájú rẹ;o kórìíra gbogbo àwọn aṣebi.

6. O máa ń pa àwọn òpùrọ́ run;OLUWA, o kórìíra àwọn apani ati ẹlẹ́tàn.

7. Ṣugbọn nípa ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,èmi óo wọ inú ilé rẹ;n óo fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ wólẹ̀, n óo sì kọjúsí tẹmpili mímọ́ rẹ.

8. OLUWA, tọ́ mi sọ́nà òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi;jẹ́ kí ọ̀nà rẹ hàn kedere níwájú mi.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 5