Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 44:18-26 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Ọkàn wa kò pada lẹ́yìn rẹ,bẹ́ẹ̀ ni a kò yẹsẹ̀ kúrò ninu ìlànà rẹ,

19. sibẹ o fọ́ wa túútúú fún ìjẹ àwọn ẹranko,o sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.

20. Bí ó bá jẹ́ pé a gbàgbé orúkọ Ọlọrun wa,tabi tí a bá bọ oriṣa,

21. ṣebí Ọlọrun ìbá ti mọ̀?Nítorí òun ni olùmọ̀ràn ọkàn.

22. Ṣugbọn nítorí tìrẹ ni wọ́n fi ń pa wá tọ̀sán-tòru,tí a kà wá sí aguntan lọ́wọ́ alápatà.

23. Para dà, OLUWA, kí ló dé tí o fi ń sùn?Jí gìrì! Má ta wá nù títí lae.

24. Kí ló dé tí o fi ń fi ojú pamọ́?Kí ló dé tí o fi gbàgbé ìpọ́njú ati ìnira wa?

25. Nítorí pé àwọn ọ̀tá ti tẹ̀ wá mọ́lẹ̀;àyà wa sì lẹ̀ mọ́lẹ̀ típẹ́típẹ́.

26. Gbéra nílẹ̀, kí o ràn wá lọ́wọ́!Gbà wá sílẹ̀ nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 44