Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 41:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń ro ti àwọn aláìní:OLUWA yóo gbà á ní ọjọ́ ìpọ́njú.

2. OLUWA yóo máa ṣọ́ ọ, yóo sì dá a sí.Yóo ní ayọ̀ ní ilẹ̀ náà;OLUWA kò ní fi í lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

3. Nígbà tí ó bá wà ní ìdùbúlẹ̀ àìsàn,OLUWA yóo fún un lókun;ní àkókò àìlera OLUWA yóo wo gbogbo àrùn rẹ̀ sàn.

4. Mo ní, “OLUWA, ṣàánú mi kí o sì wò mí sàn;mo ti ṣẹ̀ ọ́.”

Ka pipe ipin Orin Dafidi 41