Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 37:18-29 BIBELI MIMỌ (BM)

18. OLUWA a máa tọ́jú àwọn aláìlẹ́bi;ilẹ̀ ìní wọn yóo jẹ́ tiwọn títí lae.

19. Ojú kò ní tì wọ́n nígbà tí àjálù bá dé;bí ìyàn tilẹ̀ mú, wọn óo jẹ, wọn óo yó.

20. Ṣugbọn àwọn eniyan burúkú yóo ṣègbé;àwọn ọ̀tá OLUWA yóo pòórá bí ẹwà ewékowọn óo parẹ́ bí èéfín tí í parẹ́.

21. Bí eniyan burúkú bá yá owó, kò ní san;ṣugbọn ẹni rere ní ojú àánú, ó sì lawọ́.

22. Nítorí pé àwọn tí Ọlọrun bá bukun ni yóo jogún ilẹ̀ náà,ṣugbọn àwọn tí ó bá fi gégùn-ún yóo parun.

23. OLUWA níí darí ìgbésẹ̀ ẹni;a sì máa fi ẹsẹ̀ ẹni tí inú rẹ̀ bá dùn sí múlẹ̀.

24. Bí ó tilẹ̀ ṣubú, kò ní lulẹ̀ lógèdèǹgbé,nítorí OLUWA yóo gbé e ró.

25. Mo ti jẹ́ ọmọde rí; mo sì ti dàgbà:n kò tíì ri kí á kọ olódodo sílẹ̀,tabi kí ọmọ rẹ̀ máa tọrọ jẹ.

26. Olódodo ní ojú àánú, a sì máa yáni ní nǹkan,ayọ̀ ń bẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27. Ẹ yẹra fún ibi; ẹ sì máa ṣe rere;kí ẹ lè wà ní ààyè yín títí lae.

28. Nítorí OLUWA fẹ́ràn ẹ̀tọ́;kò ní kọ àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sílẹ̀.Yóo máa ṣọ́ wọn títí lae,ṣugbọn a óo pa àwọn ọmọ eniyan burúkú run.

29. Àwọn ẹni rere ni yóo jogún ilẹ̀ náà;wọn óo sì máa gbé orí rẹ̀ títí lae.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 37