Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 37:10-23 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Ẹ fún eniyan burúkú ní ìgbà díẹ̀ sí i, yóo pòórá;ẹ̀ báà wá a títí ní ààyè rẹ̀, kò ní sí níbẹ̀.

11. Ṣugbọn àwọn oníwà pẹ̀lẹ́ ni yóo jogún ilẹ̀ náà:wọn óo máa gbádùn ara wọn;wọn óo sì ní alaafia lọpọlọpọ.

12. Eniyan burúkú dìtẹ̀ mọ́ olódodo;ó sì ń wò ó bíi kíkú bíi yíyè.

13. Ṣugbọn OLUWA ń fi eniyan burúkú rẹ́rìn-ín,nítorí ó mọ̀ pé ọjọ́ ìparun rẹ̀ ń bọ̀.

14. Àwọn eniyan burúkú fa idà yọ, wọ́n sì kẹ́ ọfà wọnláti gba ẹ̀mí talaka ati aláìní,láti pa àwọn tí ń rìn lọ́nà ẹ̀tọ́.

15. Ṣugbọn idà wọn ni o óo fi pa wọ́n,ọrun wọn yóo sì dá.

16. Nǹkan díẹ̀ tí olódodo nídára ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ àwọn eniyan burúkú.

17. Nítorí OLUWA yóo ṣẹ́ apá eniyan burúkú,ṣugbọn yóo gbé olódodo ró.

18. OLUWA a máa tọ́jú àwọn aláìlẹ́bi;ilẹ̀ ìní wọn yóo jẹ́ tiwọn títí lae.

19. Ojú kò ní tì wọ́n nígbà tí àjálù bá dé;bí ìyàn tilẹ̀ mú, wọn óo jẹ, wọn óo yó.

20. Ṣugbọn àwọn eniyan burúkú yóo ṣègbé;àwọn ọ̀tá OLUWA yóo pòórá bí ẹwà ewékowọn óo parẹ́ bí èéfín tí í parẹ́.

21. Bí eniyan burúkú bá yá owó, kò ní san;ṣugbọn ẹni rere ní ojú àánú, ó sì lawọ́.

22. Nítorí pé àwọn tí Ọlọrun bá bukun ni yóo jogún ilẹ̀ náà,ṣugbọn àwọn tí ó bá fi gégùn-ún yóo parun.

23. OLUWA níí darí ìgbésẹ̀ ẹni;a sì máa fi ẹsẹ̀ ẹni tí inú rẹ̀ bá dùn sí múlẹ̀.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 37