Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 36:1-11 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ̀ṣẹ̀ ń gbin lọ́kàn eniyan burúkú,kò sí ìbẹ̀rù Ọlọrun ninu èrò tirẹ̀.

2. Nítorí pé lọ́kàn rẹ̀ a máa pọ́n ara rẹ̀,pé kò sí ẹni tí ó lè rí ẹ̀ṣẹ̀ òun,ká tó wá sọ pé yóo dá òun lẹ́bi.

3. Ọ̀rọ̀ ìkà ati ẹ̀tàn ni ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀.Ó ti dáwọ́ ire ṣíṣe dúró;kò sì hu ìwà ọlọ́gbọ́n mọ́.

4. A máa pète ìkà lórí ibùsùn rẹ̀;a máa rin ọ̀nà tí kò tọ́;kò sì kórìíra ibi.

5. OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ga kan ọ̀run;òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.

6. Òtítọ́ rẹ dàbí òkè ńlá;ìdájọ́ rẹ sì jìn bí ibú omi.OLUWA, àtènìyàn, àtẹranko ni ò ń gbàlà.

7. Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ níye lórí pupọ, Ọlọrun!Àwọn ọmọ eniyan a máa sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ.

8. Wọ́n ń rí oúnjẹ jẹ ní àjẹyó ní ilé rẹ;nǹkan mímu tí ń ṣàn bí odò,ni o sì ń fún wọn mu.

9. Nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni orísun ìyè wà;ninu ìmọ́lẹ̀ rẹ ni a ti ń rí ìmọ́lẹ̀.

10. Túbọ̀ máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀han àwọn tí ó mọ̀ ọ́,sì máa fi òdodo rẹ han àwọn ọlọ́kàn mímọ́.

11. Má jẹ́ kí àwọn agbéraga borí mi,má sì jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú lé mi kúrò.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 36