Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 35:8-17 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Jẹ́ kí ìparun dé bá wọn lójijì,jẹ́ kí àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ dè mí mú wọn;jẹ́ kí wọ́n kó sinu rẹ̀, kí wọ́n sì parun!

9. Nígbà náà ni n óo máa yọ̀ ninu OLUWA,n óo sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìgbàlà rẹ̀.

10. N óo fi gbogbo ara wí pé,“OLUWA, ta ni ó dàbí rẹ?Ìwọ ni ò ń gba aláìlágbáralọ́wọ́ ẹni tí ó lágbáratí o sì ń gba aláìlágbára ati aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ó fẹ́ fi wọ́n ṣe ìjẹ.”

11. Àwọn tí ń fi ìlara jẹ́rìí èké dìde sí mi;wọ́n ń bi mí léèrè ohun tí n kò mọ̀dí.

12. Wọ́n fi ibi san oore fún mi,ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.

13. Bẹ́ẹ̀ sì ni, ní tèmi, nígbà tí wọn ń ṣàìsàn,aṣọ ọ̀fọ̀ ni mo wọ̀;mo fi ààwẹ̀ jẹ ara mi níyà;mo gbadura pẹlu ìtẹríba patapata,

14. bí ẹni pé mò ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀rẹ́ mi, tabi arakunrin mi;mò ń lọ káàkiri, bí ẹni tí ń pohùnréré ẹkún ìyá rẹ̀,mo doríkodò, mo sì ń ṣọ̀fọ̀.

15. Ṣugbọn nígbà tí èmi kọsẹ̀, wọ́n kó ara wọn jọ,wọ́n ń yọ̀,wọ́n kó tì mí;pàápàá jùlọ, àwọn àlejò tí n kò mọ̀ ríbẹ̀rẹ̀ sí purọ́ mọ́ mi léraléra.

16. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí pẹ̀gàn mi, wọ́n ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà;wọ́n sì ń wò mí bíi pé kí n kú.

17. OLUWA, yóo ti pẹ́ tó, tí o óo máa wò mí níran?Yọ mí kúrò ninu ogun tí wọn gbé tì mí,gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn kinniun!

Ka pipe ipin Orin Dafidi 35