Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 32:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí a dárí ìrékọjá rẹ̀ jì,tí a bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀.

2. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí OLUWA kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn,tí ẹ̀tàn kò sì sí ninu ọkàn rẹ̀.

3. Nígbà tí n kò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi,ó rẹ̀ mí wá láti inú,nítorí kíkérora tí mò ń kérora ní gbogbo ìgbà.

4. Nítorí tọ̀sán-tòru ni o fi ń jẹ mí níyà;gbogbo agbára mi ló lọ háú,bí omi tíí gbẹ lákòókò ẹ̀ẹ̀rùn.

5. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún ọ;n kò sì fi àìdára mi pamọ́ fún ọ.Mo ní, “Èmi óo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Oluwa,”o sì dáríjì mí.

6. Nítorí náà, kí gbogbo olódodo máa gbadura sí ọ;ní àkókò tí ìpọ́njú bá ń yí lura wọn bí ìṣàn omi ńlá,kò ní dé ọ̀dọ̀ wọn.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 32