Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 30:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. N óo yìn ọ́, OLUWA,nítorí pé o ti yọ mí jáde;o kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.

2. OLUWA, Ọlọrun mi, mo ké pè ọ́,o sì wò mí sàn.

3. OLUWA, o ti yọ mí kúrò ninu isà òkúo sọ mí di ààyè láàrin àwọn tíwọ́n ti wọ inú kòtò.

4. Ẹ kọ orin ìyìn sí OLUWA, ẹ̀yin olùfọkànsìn rẹ̀,kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ̀.

5. Nítorí pé fún ìgbà díẹ̀ ni ibinu rẹ̀,ṣugbọn títí ayé ni ojurere rẹ̀;eniyan lè máa sọkún títí di alẹ́,ṣugbọn ayọ̀ ń bọ̀ fún un lówùúrọ̀.

6. Nígbà tí ara rọ̀ mí,mo wí ninu ọkàn mi pé,kò sí ohun tí ó lè mì mí laelae.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 30