Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 29:1-11 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi ògo fún OLUWA,ẹ gbé agbára rẹ̀ lárugẹ.

2. Ẹ fún OLUWA ní ògo tí ó yẹ orúkọ rẹ̀,ẹ máa sin OLUWA ninu ẹwà mímọ́ rẹ̀.

3. À ń gbọ́ ohùn OLUWA lójú omi òkun,Ọlọrun ológo ń sán ààrá,Ọlọrun ń sán ààrá lójú alagbalúgbú omi.

4. Ohùn OLUWA lágbára,ohùn OLUWA kún fún ọlá ńlá.

5. Ohùn OLUWA ń fọ́ igi kedari,OLUWA ń fọ́ igi kedari ti Lẹbanoni.

6. Ó ń mú kí òkè Lẹbanoni ta pọ́núnpọ́nún bí ọmọ mààlúù,ó sì mú kí òkè Sirioni máa fò bí akọ ọmọ mààlúù-igbó.

7. Ohùn OLUWA ń yọ iná lálá.

8. Ohùn OLUWA ń mi aṣálẹ̀;OLUWA ń mi aṣálẹ̀ Kadeṣi.

9. Ohùn OLUWA a máa mú abo àgbọ̀nrín bí,a máa wọ́ ewé lára igi oko;gbogbo eniyan ń kígbe ògo rẹ̀ ninu Tẹmpili rẹ̀.

10. OLUWA jókòó, ó gúnwà lórí ìkún omi;OLUWA jókòó, ó gúnwà bí ọba títí lae.

11. OLUWA yóo fún àwọn eniyan rẹ̀ ní agbára;OLUWA yóo fún wọn ní ibukun alaafia.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 29