Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 26:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Dá mi láre, OLUWA,nítorí ninu ìwà pípé ni mò ń rìn,mo sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA láìṣiyèméjì.

2. Yẹ̀ mí wò, OLUWA, dán mi wò;yẹ inú mi wò, sì ṣe akiyesi ọkàn mi.

3. Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ni mo tẹjúmọ́,mo sì ń fi òtítọ́ bá ọ rìn.

4. N kò jókòó ti àwọn èké,n kò sì gba ìmọ̀ràn àwọn ẹlẹ́tàn;

5. mo kórìíra wíwà pẹlu àwọn aṣebi,n kò sì jẹ́ bá àwọn eniyan burúkú da nǹkan pọ̀.

6. Ọwọ́ mi mọ́, n kò ní ẹ̀bi, OLUWA,mo sì ń jọ́sìn yí pẹpẹ rẹ ká.

7. Mò ń kọ orin ọpẹ́ sókè,mo sì ń ròyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ.

8. OLUWA, mo fẹ́ràn ilé rẹ, tí ò ń gbé,ati ibi tí ògo rẹ wà.

9. Má pa mí run pẹlu àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,má sì gba ẹ̀mí mi pẹlu ti àwọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ ìpànìyàn,

Ka pipe ipin Orin Dafidi 26