Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 25:7-20 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Má ranti ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ti ṣẹ̀ ní ìgbà èwe mi,tabi ibi tí mo ti kọjá ààyè mi;ranti mi, OLUWA, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,ati nítorí oore rẹ.

8. Olóore ati olódodo ni OLÚWA,nítorí náà ni ó ṣe ń fi ọ̀nà han àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

9. A máa tọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́,a sì máa kọ́ wọn ní ìlànà rẹ̀.

10. Gbogbo ọ̀nà OLUWA ni ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́,fún àwọn tí ń pa majẹmu ati òfin rẹ̀ mọ́.

11. Nítorí orúkọ rẹ, OLUWA, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí,nítorí mo jẹ̀bi lọpọlọpọ.

12. Ẹni tí ó bá bẹ̀rù OLUWAni OLUWA yóo kọ́ ní ọ̀nà tí yóo yàn.

13. Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yóo ní ọpọlọpọ ọrọ̀,àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóo sì jogún ilẹ̀ náà.

14. Àwọn tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni OLUWA ń mú ní ọ̀rẹ́,a sì máa fi majẹmu rẹ̀ hàn wọ́n.

15. OLUWA ni mò ń wò lójú nígbà gbogbo,nítorí òun ni yóo yọ ẹsẹ̀ mi kúrò ninu àwọ̀n.

16. Kọjú sí mi kí o sì ṣàánú mi;nítorí n kò lẹ́nìkan, ojú sì ń pọ́n mi.

17. Mú ìdààmú ọkàn mi kúrò;kí o sì yọ mí ninu gbogbo ìpọ́njú mi.

18. Wo ìpọ́njú ati ìdààmú mi,kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí.

19. Wo iye ọ̀tá tí èmi nìkan ní,ati irú ìkórìíra ìkà tí wọ́n kórìíra mi.

20. Pa mí mọ́, kí o sì gbà mí;má jẹ́ kí ojú kí ó tì mí,nítorí ìwọ ni mo sá di.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 25