Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 25:3-17 BIBELI MIMỌ (BM)

3. OLUWA, má jẹ́ kí ojú ó ti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọ;àwọn ọ̀dàlẹ̀ eniyan ni kí ojú ó tì.

4. Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, OLUWA,kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ.

5. Tọ́ mi sí ọ̀nà òtítọ́ rẹ, sì máa kọ́ mi,nítorí ìwọ ni Ọlọrun olùgbàlà mi;ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé ní ọjọ́ gbogbo.

6. OLUWA, ranti àánú rẹ, ati ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,nítorí wọ́n ti wà ọjọ́ ti pẹ́.

7. Má ranti ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ti ṣẹ̀ ní ìgbà èwe mi,tabi ibi tí mo ti kọjá ààyè mi;ranti mi, OLUWA, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,ati nítorí oore rẹ.

8. Olóore ati olódodo ni OLÚWA,nítorí náà ni ó ṣe ń fi ọ̀nà han àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

9. A máa tọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́,a sì máa kọ́ wọn ní ìlànà rẹ̀.

10. Gbogbo ọ̀nà OLUWA ni ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́,fún àwọn tí ń pa majẹmu ati òfin rẹ̀ mọ́.

11. Nítorí orúkọ rẹ, OLUWA, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí,nítorí mo jẹ̀bi lọpọlọpọ.

12. Ẹni tí ó bá bẹ̀rù OLUWAni OLUWA yóo kọ́ ní ọ̀nà tí yóo yàn.

13. Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yóo ní ọpọlọpọ ọrọ̀,àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóo sì jogún ilẹ̀ náà.

14. Àwọn tí ó bá bẹ̀rù OLUWA ni OLUWA ń mú ní ọ̀rẹ́,a sì máa fi majẹmu rẹ̀ hàn wọ́n.

15. OLUWA ni mò ń wò lójú nígbà gbogbo,nítorí òun ni yóo yọ ẹsẹ̀ mi kúrò ninu àwọ̀n.

16. Kọjú sí mi kí o sì ṣàánú mi;nítorí n kò lẹ́nìkan, ojú sì ń pọ́n mi.

17. Mú ìdààmú ọkàn mi kúrò;kí o sì yọ mí ninu gbogbo ìpọ́njú mi.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 25