Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 21:9-13 BIBELI MIMỌ (BM)

9. O óo jó wọn run bí iná ìléru, nígbà tí o bá yọ sí wọn.OLUWA yóo gbé wọn mì ninu ibinu rẹ̀;iná yóo sì jó wọn ní àjórun.

10. O óo pa àwọn ọmọ wọn run lórí ilẹ̀ ayé,o óo sì run ìran wọn láàrin àwọn eniyan.

11. Bí wọn bá gbèrò ibi sí ọ,tí wọ́n sì pète ìkà, wọn kò ní lè ṣe é.

12. Nítorí pé o óo lé wọn sá;nígbà tí o bá fi ọfà rẹ sun ojú wọn.

13. A gbé ọ ga, nítorí agbára rẹ, OLUWA!A óo máa kọrin, a óo sì máa yin agbára rẹ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 21