Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 16:4-11 BIBELI MIMỌ (BM)

4. “Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀:Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ,bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”

5. OLUWA, ìwọ ni ìpín mi, ìwọ ni mo yàn;ìwọ ni ò ń jẹ́ kí ọ̀ràn mi fìdí múlẹ̀.

6. Ìpín tí ó bọ́ sí mi lọ́wọ́ dára pupọ;ogún rere ni ogún ti mo jẹ.

7. Èmi óo máa yin OLUWA, ẹni tí ó ń fún mi ní òye;ọkàn mi ó sì máa tọ́ mi sọ́nà ní òròòru.

8. Mò ń wo OLUWA ní iwájú mi nígbà gbogbo,nítorí pé Ọlọrun dúró tì mí, ẹsẹ̀ mi kò ní yẹ̀.

9. Nítorí náà ni ọkàn mi ṣe ń yọ̀, tí inú mi dùn;ara sì rọ̀ mí.

10. Nítorí o kò ní gbàgbé mi sí ipò òkú,bẹ́ẹ̀ ni o kò ní jẹ́ kí ẹni tí ó fi tọkàntọkàn sìn ọ́ rí ìdíbàjẹ́.

11. O ti fi ọ̀nà ìyè hàn mí;ayọ̀ kíkún ń bẹ ní iwájú rẹ,ìgbádùn àìlópin sì ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 16