Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 147:4-20 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Òun ló mọ iye àwọn ìràwọ̀,òun ló sì fún gbogbo wọn lórúkọ.

5. OLUWA wa tóbi, ó sì lágbára pupọòye rẹ̀ kò ní ìwọ̀n.

6. OLUWA ní ń gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ró,òun ni ó sì ń sọ àwọn eniyan burúkú di ilẹ̀ẹ́lẹ̀.

7. Ẹ kọ orin ọpẹ́ sí OLUWA,ẹ fi hapu kọ orin dídùn sí Ọlọrun wa.

8. Ẹni tí ó fi ìkùukùu bo ojú ọ̀run,ó pèsè òjò fún ilẹ̀,ó mú koríko hù lórí òkè.

9. Òun ni ó ń fún àwọn ẹranko ní oúnjẹ,tí ó sì ń bọ́ ọmọ ẹyẹ ìwò, tí ó ń ké.

10. Kì í ṣe agbára ẹṣin ni inú rẹ̀ dùn sí,kì í sì í ṣe inú agbára eniyan ni ayọ̀ rẹ̀ wà.

11. Ṣugbọn inú OLUWA dùn sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,àwọn tí ó ní ìrètí ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

12. Gbé OLUWA ga, ìwọ Jerusalẹmu!Yin Ọlọrun rẹ, ìwọ Sioni!

13. Ó fún ẹnubodè rẹ ní agbára,ó sì bukun àwọn tí ń gbé inú rẹ.

14. Ó jẹ́ kí alaafia wà ní ààlà ilẹ̀ rẹ,ó sì fi oúnjẹ tí ó dára bọ́ ọ lábọ̀ọ́yó.

15. Ó pàṣẹ lórí ilẹ̀ ayé,àṣẹ rẹ̀ sì múlẹ̀ kíá.

16. Ó da òjò dídì bo ilẹ̀ bí ẹ̀gbọ̀n òwú,ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú.

17. Ó sọ yìnyín sílẹ̀ bí òkò,ta ni ó lè fara da òtútù rẹ̀?

18. Ó sọ̀rọ̀, wọ́n yọ́,ó fẹ́ afẹ́fẹ́, omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn.

19. Ó ṣí ọ̀rọ̀ rẹ̀ payá fún Jakọbu,ó sì fi òfin ati ìlànà rẹ̀ han Israẹli.

20. Kò ṣe bẹ́ẹ̀ fún orílẹ̀-èdè kankan rí,wọn kò sì mọ ìlànà rẹ̀.Ẹ yin OLUWA!

Ka pipe ipin Orin Dafidi 147