1. Ẹ yin OLUWA!Nítorí tí ó dára láti máa kọ orin ìyìn sí Ọlọrun wa;nítorí olóore ni, orin ìyìn sì yẹ ẹ́.
2. OLUWA ní ń kọ́ ìlú Jerusalẹmu;òun ni yóo kó àwọn ọmọ Israẹli tí a fọ́n ká jọ.
3. Ó ń tu àwọn tí ọkàn wọn bàjẹ́ ninu,ó sì ń dí ọgbẹ́ wọn.
4. Òun ló mọ iye àwọn ìràwọ̀,òun ló sì fún gbogbo wọn lórúkọ.
5. OLUWA wa tóbi, ó sì lágbára pupọòye rẹ̀ kò ní ìwọ̀n.