Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 136:3-13 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA tí ó ju gbogbo àwọn oluwa lọ,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

4. Òun nìkan ṣoṣo ní ń ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

5. Ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

6. ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lé orí omi,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

7. ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

8. Ó dá oòrùn láti máa ṣe àkóso ọ̀sán,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

9. Ó dá òṣùpá ati ìràwọ̀ láti máa ṣe àkóso òru,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

10. Ẹni tí ó pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

11. ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láàrin wọn,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

12. Pẹlu ipá ati ọwọ́ líle ni ó fi kó wọn jáde,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

13. Ẹni tí ó pín Òkun Pupa sí meji,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

Ka pipe ipin Orin Dafidi 136