Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 136:12-26 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Pẹlu ipá ati ọwọ́ líle ni ó fi kó wọn jáde,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

13. Ẹni tí ó pín Òkun Pupa sí meji,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

14. ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli kọjá láàrin rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

15. ṣugbọn ó bi Farao ati àwọn ọmọ ogunrẹ̀ ṣubú ninu Òkun Pupa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

16. Ẹni tí ó mú àwọn eniyan rẹ̀ la aṣálẹ̀ já,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

17. ẹni tí ó pa àwọn ọba ńlá,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

18. ó sì pa àwọn ọba olókìkí,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

19. Sihoni ọba àwọn Amori,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

20. ati Ogu ọba Baṣani,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

21. Ó pín ilẹ̀ wọn fún àwọn eniyan rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

22. ó fún àwọn ọmọ Israẹli, iranṣẹ rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

23. Òun ni ó ranti wa ní ipò ìrẹ̀lẹ̀ wa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;

24. ó sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

25. Ẹni tí ó pèsè oúnjẹ fún gbogbo ẹ̀dá alààyè,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

26. Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọrun ọ̀run,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 136