Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 135:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ yin OLUWA.Ẹ yin orúkọ OLUWA;ẹ yìn ín, ẹ̀yin iranṣẹ rẹ̀,

2. ẹ̀yin tí ẹ̀ ń jọ́sìn ninu ilé OLUWA,tí ẹ wà ní àgbàlá ilé Ọlọrun wa.

3. Ẹ yin OLUWA, nítorí pé ó ṣeun;ẹ kọrin ìyìn sí i,nítorí pé olóore ọ̀fẹ́ ni.

4. Nítorí pé OLUWA ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀,ó ti yan Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.

5. Èmi mọ̀ pé OLUWA tóbi,ati pé ó ju gbogbo oriṣa lọ.

6. Bí ó ti wu OLUWA ni ó ń ṣelọ́run ati láyé,ninu òkun ati ninu ibú.

7. Òun ló gbá ìkùukùu jọ láti òpin ilẹ̀ ayé,ó fi mànàmáná fún òjò,ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti inú ilé ìṣúra rẹ̀.

8. Òun ló pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti,ati teniyan ati tẹran ọ̀sìn.

9. Ẹni tí ó rán iṣẹ́ abàmì ati iṣẹ́ ìyanu sí ilẹ̀ Ijipti,ó rán sí Farao ati gbogbo àwọn iranṣẹ rẹ̀.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 135