Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 119:83-96 BIBELI MIMỌ (BM)

83. Mo dàbí agbè ọtí tí ó ti di àlòpatì,sibẹ, n kò gbàgbé ìlànà rẹ.

84. Èmi iranṣẹ rẹ yóo ti dúró pẹ́ tó?Nígbà wo ni ìwọ óo dájọ́ fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi?

85. Àwọn onigbeeraga ti gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí,àní, àwọn tí kì í pa òfin rẹ mọ́.

86. Gbogbo òfin rẹ ló dájú;ràn mí lọ́wọ́, nítorí wọ́n ń fi ìwà èké ṣe inúnibíni mi.

87. Wọ́n fẹ́rẹ̀ pa mí run láyé,ṣugbọn n kò kọ ìlànà rẹ sílẹ̀.

88. Dá ẹ̀mí mi sí gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,kí n lè máa mú gbogbo àṣẹ rẹ ṣẹ.

89. OLUWA, títí lae ni ọ̀rọ̀ rẹ fìdí múlẹ̀ lọ́run.

90. Òtítọ́ rẹ wà láti ìrandíran;o ti fi ìdí ayé múlẹ̀, ó sì dúró.

91. Ohun gbogbo wà gẹ́gẹ́ bí ìlànà rẹ, títí di òní,nítorí pé iranṣẹ rẹ ni gbogbo wọn.

92. Bí kò bá jẹ́ pé òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi,ǹ bá ti ṣègbé ninu ìpọ́njú.

93. Lae, n kò ní gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ,nítorí pé, nípasẹ̀ wọn ni o fi mú mi wà láyé.

94. Ìwọ ni o ni mí, gbà mí;nítorí pé mo ti kọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.

95. Àwọn eniyan burúkú ba dè mí,wọ́n fẹ́ pa mí run,ṣugbọn mò ń ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

96. Mo ti rí i pé kò sí ohun tí ó lè pé tán,àfi òfin rẹ nìkan ni kò lópin.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 119