Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 119:77-91 BIBELI MIMỌ (BM)

77. Ṣàánú mi, kí n lè wà láàyè,nítorí pé òfin rẹ ni ìdùnnú mi.

78. Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn onigbeeraga,nítorí wọ́n ṣe àrékérekè sí mi láìnídìí;ní tèmi, n óo máa ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

79. Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ tọ̀ mí wá,kí wọ́n lè mọ òfin rẹ.

80. Níti pípa òfin rẹ mọ́, jẹ́ kí n pé,kí ojú má baà tì mí.

81. Mo wá ìgbàlà rẹ títí, àárẹ̀ mú ọkàn mi;ṣugbọn mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

82. Mo fojú sọ́nà títí, agara dá mi,níbi tí mo tí ń retí ìmúṣẹ ìlérí rẹ.Mo ní, “Nígbà wo ni o óo tù mí ninu?”

83. Mo dàbí agbè ọtí tí ó ti di àlòpatì,sibẹ, n kò gbàgbé ìlànà rẹ.

84. Èmi iranṣẹ rẹ yóo ti dúró pẹ́ tó?Nígbà wo ni ìwọ óo dájọ́ fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi?

85. Àwọn onigbeeraga ti gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí,àní, àwọn tí kì í pa òfin rẹ mọ́.

86. Gbogbo òfin rẹ ló dájú;ràn mí lọ́wọ́, nítorí wọ́n ń fi ìwà èké ṣe inúnibíni mi.

87. Wọ́n fẹ́rẹ̀ pa mí run láyé,ṣugbọn n kò kọ ìlànà rẹ sílẹ̀.

88. Dá ẹ̀mí mi sí gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,kí n lè máa mú gbogbo àṣẹ rẹ ṣẹ.

89. OLUWA, títí lae ni ọ̀rọ̀ rẹ fìdí múlẹ̀ lọ́run.

90. Òtítọ́ rẹ wà láti ìrandíran;o ti fi ìdí ayé múlẹ̀, ó sì dúró.

91. Ohun gbogbo wà gẹ́gẹ́ bí ìlànà rẹ, títí di òní,nítorí pé iranṣẹ rẹ ni gbogbo wọn.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 119