Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 119:57-66 BIBELI MIMỌ (BM)

57. OLUWA, ìwọ nìkan ni mo ní;mo ṣe ìlérí láti pa òfin rẹ mọ́.

58. Tọkàntọkàn ni mò ń wá ojurere rẹ,ṣe mí lóore gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

59. Nígbà tí mo ronú nípa ìṣe mi,mo yipada sí ìlànà rẹ;

60. mo yára, bẹ́ẹ̀ ni n kò lọ́ra láti pa òfin rẹ mọ́.

61. Bí okùn àwọn eniyan burúkú tilẹ̀ wé mọ́ mi,n kò ní gbàgbé òfin rẹ.

62. Mo dìde lọ́gànjọ́ láti yìn ọ́,nítorí ìlànà òdodo rẹ.

63. Ọ̀rẹ́ gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ ni mí,àní, àwọn tí wọn ń pa òfin rẹ mọ́.

64. OLUWA, ayé kún fún ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀;kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

65. OLUWA, o ti ṣeun fún èmi iranṣẹ rẹ,gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

66. Fún mi ní òye ati ìmọ̀ pípé,nítorí mo ní igbagbọ ninu àṣẹ rẹ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 119