Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 119:39-56 BIBELI MIMỌ (BM)

39. Mú ẹ̀gàn tí ń bà mí lẹ́rù kúrò,nítorí pé ìlànà rẹ dára.

40. Wò ó, ọkàn mi fà sí ati máa tẹ̀lé ìlànà rẹ,sọ mí di alààyè nítorí òdodo rẹ!

41. Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn mí, OLÚWA,kí o sì gbà mí là gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

42. Nígbà náà ni n óo lè dá àwọn tí ń gàn mí lóhùn,nítorí mo gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

43. Má gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ rẹ lẹ́nu mi rárá,nítorí ìrètí mi ń bẹ ninu ìlànà rẹ.

44. N óo máa pa òfin rẹ mọ́ nígbà gbogbo, lae ati laelae.

45. N óo máa rìn fàlàlà,nítorí pé mo tẹ̀lé ìlànà rẹ.

46. N óo máa sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba,ojú kò sì ní tì mí.

47. Mo láyọ̀ ninu òfin rẹ,nítorí tí mo fẹ́ràn rẹ̀.

48. Mo bọ̀wọ̀ fún àṣẹ rẹ tí mo fẹ́ràn,n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.

49. Ranti ọ̀rọ̀ tí o bá èmi iranṣẹ rẹ sọ,èyí tí ó fún mi ní ìrètí.

50. Ohun tí ó ń tù mí ninu ní àkókò ìpọ́njú ni pé:ìlérí rẹ mú mi wà láàyè.

51. Àwọn onigbeeraga ń kẹ́gàn mi gidigidi,ṣugbọn n ò kọ òfin rẹ sílẹ̀.

52. Mo ranti òfin rẹ àtijọ́,OLUWA, ọkàn mi sì balẹ̀.

53. Inú mi á máa ru,nígbà tí mo bá rí àwọn eniyan burúkú,tí wọn ń rú òfin rẹ.

54. Òfin rẹ ni mò ń fi ń ṣe orin kọ,lákòókò ìrìn àjò mi láyé.

55. Mo ranti orúkọ rẹ lóru;OLUWA, mo sì pa òfin rẹ mọ́:

56. Èyí ni ìṣe mi:Èmi a máa pa òfin rẹ mọ́.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 119