Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 119:35-48 BIBELI MIMỌ (BM)

35. Tọ́ mi sí ọ̀nà nípa òfin rẹ,nítorí pé mo láyọ̀ ninu rẹ̀.

36. Mú kí ọkàn mi fà sí òfin rẹ,kí ó má fà sí ọrọ̀ ayé.

37. Yí ojú mi kúrò ninu wíwo nǹkan asán,sọ mí di alààyè ní ọ̀nà rẹ.

38. Mú ìlérí rẹ ṣẹ fún iranṣẹ rẹ,àní, ìlérí tí o ṣe fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ.

39. Mú ẹ̀gàn tí ń bà mí lẹ́rù kúrò,nítorí pé ìlànà rẹ dára.

40. Wò ó, ọkàn mi fà sí ati máa tẹ̀lé ìlànà rẹ,sọ mí di alààyè nítorí òdodo rẹ!

41. Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn mí, OLÚWA,kí o sì gbà mí là gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

42. Nígbà náà ni n óo lè dá àwọn tí ń gàn mí lóhùn,nítorí mo gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

43. Má gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ rẹ lẹ́nu mi rárá,nítorí ìrètí mi ń bẹ ninu ìlànà rẹ.

44. N óo máa pa òfin rẹ mọ́ nígbà gbogbo, lae ati laelae.

45. N óo máa rìn fàlàlà,nítorí pé mo tẹ̀lé ìlànà rẹ.

46. N óo máa sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba,ojú kò sì ní tì mí.

47. Mo láyọ̀ ninu òfin rẹ,nítorí tí mo fẹ́ràn rẹ̀.

48. Mo bọ̀wọ̀ fún àṣẹ rẹ tí mo fẹ́ràn,n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 119