Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 119:33-42 BIBELI MIMỌ (BM)

33. OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ,n óo sì pa wọ́n mọ́ dé òpin.

34. Là mí lóye, kí n lè máa pa òfin rẹ mọ́,kí n sì máa fi tọkàntọkàn pa wọ́n mọ́.

35. Tọ́ mi sí ọ̀nà nípa òfin rẹ,nítorí pé mo láyọ̀ ninu rẹ̀.

36. Mú kí ọkàn mi fà sí òfin rẹ,kí ó má fà sí ọrọ̀ ayé.

37. Yí ojú mi kúrò ninu wíwo nǹkan asán,sọ mí di alààyè ní ọ̀nà rẹ.

38. Mú ìlérí rẹ ṣẹ fún iranṣẹ rẹ,àní, ìlérí tí o ṣe fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ.

39. Mú ẹ̀gàn tí ń bà mí lẹ́rù kúrò,nítorí pé ìlànà rẹ dára.

40. Wò ó, ọkàn mi fà sí ati máa tẹ̀lé ìlànà rẹ,sọ mí di alààyè nítorí òdodo rẹ!

41. Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn mí, OLÚWA,kí o sì gbà mí là gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

42. Nígbà náà ni n óo lè dá àwọn tí ń gàn mí lóhùn,nítorí mo gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 119