Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 118:1-10 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ OLUWA, nítorí pé ó ṣeun,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.

2. Jẹ́ kí Israẹli wí pé,“Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”

3. Kí àwọn ará ilé Aaroni wí pé,“Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”

4. Kí àwọn tí ó bẹ̀rù OLUWA wí pé,“Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.”

5. Ninu ìpọ́njú, mo ké pe OLUWA,ó dá mi lóhùn, ó sì tú mi sílẹ̀.

6. Nígbà tí OLUWA wà pẹlu mi, ẹ̀rù kò bà mí.Kí ni eniyan lè fi mí ṣe?

7. OLUWA wà pẹlu mi láti ràn mí lọ́wọ́,nítorí náà, n óo wo àwọn tí wọ́n kórìíra mipẹlu ayọ̀ ìṣẹ́gun.

8. Ó sàn láti sá di OLUWA,ju ati gbẹ́kẹ̀lé eniyan lọ.

9. Ó sàn láti sá di OLUWA,ju ati gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìjòyè.

10. Gbogbo orílẹ̀-èdè dòòyì ká mi,ṣugbọn ní orúkọ OLUWA, mo pa wọ́n run!

Ka pipe ipin Orin Dafidi 118