Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 116:7-13 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Sinmi ìwọ ọkàn mi, bíi ti àtẹ̀yìnwá,nítorí pé OLUWA ṣeun fún ọ lọpọlọpọ.

8. Nítorí ìwọ OLUWA ti gba ọkàn mi lọ́wọ́ ikú,o gba ojú mi lọ́wọ́ omijé,o sì gba ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú.

9. Mò ń rìn níwájú OLUWA, lórí ilẹ̀ alààyè.

10. Igbagbọ mi kò yẹ̀, nígbà tí mo tilẹ̀ wí pé,“Ìpọ́njú dé bá mi gidigidi.”

11. Mo wí ninu ìdààmú ọkàn pé,“Èké ni gbogbo eniyan.”

12. Kí ni n óo san fún OLUWA,nítorí gbogbo oore rẹ̀ lórí mi?

13. N óo mu ẹbọ nǹkan mímu wá fún OLUWA,n óo sì pe orúkọ rẹ̀.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 116