Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 109:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Má dákẹ́, ìwọ Ọlọrun tí mò ń yìn.

2. Nítorí pé ẹnu àwọn eniyan burúkú ati tiàwọn ẹlẹ́tàn kò dákẹ́,wọ́n ń sọ̀rọ̀ èké nípa mi.

3. Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ káàkiri nípa mi,wọ́n sì ń gbógun tì mí láìnídìí.

4. Èmi fẹ́ràn wọn; ṣugbọn ẹ̀sùn ni wọ́n fi ń kàn mí,sibẹ, adura ni mò ń gbà fún wọn.

5. Ibi ni wọ́n fí ń san oore fún mi,ìkórìíra ni wọ́n sì fi ń san ìfẹ́ tí mo ní sí wọn.

6. Yan eniyan burúkú tì í,jẹ́ kí ẹlẹ́sùn èké kó o sẹ́jọ́.

7. Nígbà tí a bá ń dá ẹjọ́ rẹ̀,jẹ́ kí wọn dá a lẹ́bi;kí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ di ọ̀ràn sí i lọ́rùn.

8. Ṣe é ní ẹlẹ́mìí kúkúrú,kí ohun ìní rẹ̀ di ti àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà.

9. Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìníbaba,kí aya rẹ̀ di opó.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 109