Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 109:1-10 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Má dákẹ́, ìwọ Ọlọrun tí mò ń yìn.

2. Nítorí pé ẹnu àwọn eniyan burúkú ati tiàwọn ẹlẹ́tàn kò dákẹ́,wọ́n ń sọ̀rọ̀ èké nípa mi.

3. Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ káàkiri nípa mi,wọ́n sì ń gbógun tì mí láìnídìí.

4. Èmi fẹ́ràn wọn; ṣugbọn ẹ̀sùn ni wọ́n fi ń kàn mí,sibẹ, adura ni mò ń gbà fún wọn.

5. Ibi ni wọ́n fí ń san oore fún mi,ìkórìíra ni wọ́n sì fi ń san ìfẹ́ tí mo ní sí wọn.

6. Yan eniyan burúkú tì í,jẹ́ kí ẹlẹ́sùn èké kó o sẹ́jọ́.

7. Nígbà tí a bá ń dá ẹjọ́ rẹ̀,jẹ́ kí wọn dá a lẹ́bi;kí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ di ọ̀ràn sí i lọ́rùn.

8. Ṣe é ní ẹlẹ́mìí kúkúrú,kí ohun ìní rẹ̀ di ti àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà.

9. Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìníbaba,kí aya rẹ̀ di opó.

10. Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di alárìnká,kí wọn máa ṣagbe kiri;kí á lé wọn jáde kúrò ninu ahoro tí wọn ń gbé.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 109