6. Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn,ó sì yọ wọ́n kúrò ninu ìṣẹ́ wọn.
7. Ó kó wọn gba ọ̀nà tààrà jáde,lọ sí ìlú tí wọ́n lè máa gbé.
8. Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,àní nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún àwọn ọmọ eniyan.
9. Nítorí pé ó fi omi tẹ́ àwọn tí òùngbẹ ń gbẹ lọ́rùn,ó sì fi oúnjẹ dáradára bọ́ àwọn tí ebi ń pa ní àbọ́yó.
10. Àwọn kan jókòó ninu òkùnkùn pẹlu ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn,wọ́n wà ninu ìgbèkùn ati ìpọ́njú, a sì fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè wọ́n,
11. nítorí pé wọ́n tàpá sí òfin Ọlọrun,wọ́n sì pẹ̀gàn ìmọ̀ràn ọ̀gá ògo.
12. Làálàá mú kí agara dá ọkàn wọn,wọ́n ṣubú lulẹ̀ láìsí olùrànlọ́wọ́.