Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 106:20-29 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Wọ́n gbé ògo Ọlọrunfún ère mààlúù tí ń jẹ koríko.

21. Wọ́n gbàgbé Ọlọrun, Olùgbàlà wọn,tí ó ṣe iṣẹ́ ribiribi ní Ijipti,

22. ó ṣe, iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu,ati ohun ẹ̀rù lẹ́bàá òkun pupa.

23. Nítorí náà ni ó ṣe wí pé òun yóo pa wọ́n run,bí kì í bá ṣe ti Mose, àyànfẹ́ rẹ̀,tí ó dúró níwájú rẹ̀, tí ó sì ṣìpẹ̀,láti yí ibinu OLUWA pada, kí ó má baà pa wọ́n run.

24. Wọn kò bìkítà fún ilẹ̀ dáradára náà,wọn kò sì ní igbagbọ ninu ọ̀rọ̀ OLUWA.

25. Wọ́n ń kùn ninu àgọ́ wọn,wọn kò sì fetí sí ohùn OLUWA.

26. Nítorí náà, ó gbé ọwọ́ sókè, ó búra fún wọnpé òun yóo jẹ́ kí wọ́n kú sí aṣálẹ̀,

27. ati pé òun yóo fọ́n àwọn ìran wọn káàkiriàwọn orílẹ̀-èdè.

28. Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali ti Peori,wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí wọ́n rú sí òkú.

29. Wọ́n fi ìwà burúkú wọn mú OLUWA bínú,àjàkálẹ̀ àrùn sì bẹ́ sílẹ̀ láàrin wọn.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 106