Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 105:28-39 BIBELI MIMỌ (BM)

28. Ọlọrun rán òkùnkùn, ilẹ̀ sì ṣú,ṣugbọn wọ́n ṣe oríkunkun sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

29. Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀,ó sì mú kí ẹja wọn kú.

30. Ọ̀pọ̀lọ́ ń tú jáde ní ilẹ̀ wọn,títí kan ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.

31. Ọlọrun sọ̀rọ̀, eṣinṣin sì rọ́ dé,iná aṣọ sì bo gbogbo ilẹ̀ wọn.

32. Ó rọ̀jò yìnyín lé wọn lórí,mànàmáná sì ń kọ káàkiri ilẹ̀ wọn.

33. Ó kọlu àjàrà ati igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn,ó sì wó àwọn igi ilẹ̀ wọn.

34. Ó sọ̀rọ̀, àwọn eṣú sì rọ́ dé,ati àwọn tata tí kò lóǹkà;

35. wọ́n jẹ gbogbo ewé tí ó wà ní ilẹ̀ wọn,ati gbogbo èso ilẹ̀ náà.

36. Ó kọlu gbogbo àkọ́bí ilẹ̀ wọn,àní, gbogbo àrẹ̀mọ ilẹ̀ wọn.

37. Lẹ́yìn náà, ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde,tàwọn ti fadaka ati wúrà,kò sì sí ẹnikẹ́ni ninu ẹ̀yà kankan tí ó ṣe àìlera.

38. Inú àwọn ará Ijipti dùn nígbà tí wọ́n jáde,nítorí ẹ̀rù àwọn ọmọ Israẹli ń bà wọ́n.

39. OLUWA ta ìkùukùu bò wọ́n,ó sì pèsè iná láti tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn lóru.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 105