Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 104:21-32 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun ń bú fún ìjẹ,wọ́n ń wo ojú Ọlọrun fún oúnjẹ.

22. Nígbà tí oòrùn bá là, wọn á wọ́ lọ;wọn á lọ dùbúlẹ̀ sinu ihò wọn.

23. Ọmọ eniyan á sì jáde lọ síbi iṣẹ́ rẹ̀,á lọ síbi làálàá rẹ̀ títí di àṣáálẹ́.

24. OLUWA, ìyanu ni iṣẹ́ ọwọ́ rẹ!Ọgbọ́n ni o fi dá gbogbo wọn.Ayé kún fún àwọn ẹ̀dá rẹ.

25. Ẹ wo òkun bí ó ti tóbi tí ó sì fẹ̀,ó kún fún ọ̀kẹ́ àìmọye ẹ̀dá,nǹkan abẹ̀mí kéékèèké ati ńláńlá.

26. Ibẹ̀ ni ọkọ̀ ojú omi ń gbà lọ,ati Lefiatani tí o dá láti máa ṣeré ninu òkun.

27. Ojú rẹ ni gbogbo wọn ń wò,fún ìpèsè oúnjẹ ní àkókò.

28. Nígbà tí o bá fún wọn, wọn á kó o jọ,nígbà tí o bá la ọwọ́,wọn á jẹ ohun dáradára ní àjẹyó.

29. Bí o bá fojú pamọ́,ẹ̀rù á bà wọ́n,bí o bá gba ẹ̀mí wọn, wọn á kú,wọn á sì pada di erùpẹ̀.

30. Nígbà tí o rán ẹ̀mí rẹ jáde,wọ́n di ẹ̀dá alààyè,o sì sọ orí ilẹ̀ di ọ̀tun.

31. Kí ògo OLUWA máa wà títí lae,kí OLUWA máa yọ̀ ninu iṣẹ́ rẹ̀.

32. Ẹni tí ó wo ilẹ̀, tí ilẹ̀ mì tìtì,tí ó fọwọ́ kan òkè, tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí yọ èéfín.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 104