Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 103:2-19 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi,má sì ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,

3. ẹni tí ó ń dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́,tí ó ń wo gbogbo àrùn rẹ sàn;

4. ẹni tí ó ń yọ ẹ̀mí rẹ kúrò ninu ọ̀fìn,tí ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ati àánú dé ọ ládé.

5. Ẹni tí ó ń fi ohun dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn,tí ó fi ń sọ agbára ìgbà èwe rẹ dọ̀tun bíi ti idì.

6. OLUWA a máa dáni lárea sì máa ṣe ìdájọ́ òdodo fún gbogboàwọn tí a ni lára.

7. Ó fi ọ̀nà rẹ̀ han Mose,ó sì ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ han àwọn ọmọ Israẹli.

8. Aláàánú ati olóore ni OLUWA,kì í tètè bínú, ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀.

9. Kì í fi ìgbà gbogbo báni wí,bẹ́ẹ̀ ni ibinu rẹ̀ kì í pẹ́ títí ayé.

10. Kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa,bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa bí àìdára wa.

11. Nítorí bí ọ̀run ti jìnnà sí ilẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ṣe tóbi tósí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

12. Bí ìlà oòrùn ti jìnnà sí ìwọ oòrùn,bẹ́ẹ̀ ni ó mú ẹ̀ṣẹ̀ wa jìnnà sí wa.

13. Bí baba ti máa ń ṣàánú àwọn ọmọ rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni OLUWA máa ń ṣàánú àwọntí ó bá bẹ̀rù rẹ̀.

14. Nítorí ó mọ ẹ̀dá wa;ó ranti pé erùpẹ̀ ni wá.

15. Ọjọ́ ayé ọmọ eniyan dàbí ti koríko,eniyan a sì máa gbilẹ̀ bí òdòdó inú igbó;

16. ṣugbọn bí afẹ́fẹ́ bá ti fẹ́ kọjá lórí rẹ̀,á rẹ̀ dànù,ààyè rẹ̀ kò sì ní ranti rẹ̀ mọ́.

17. Ṣugbọn títí ayé ni ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀,sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,òdodo rẹ̀ wà lára arọmọdọmọ wọn.

18. Ó wà lára àwọn tí ó ń pa majẹmu rẹ̀ mọ́,tí wọn sì ń ranti láti pa òfin rẹ̀ mọ́.

19. OLUWA ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ lọ́run,ó sì jọba lórí ohun gbogbo.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 103