Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 10:11-18 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Ó sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun ti gbàgbé,OLUWA ti gbé ojú kúrò, kò sì ní rí i laelae.”

12. Dìde, OLUWA; Ọlọrun, wá nǹkankan ṣe sí i;má sì gbàgbé àwọn tí a nilára.

13. Kí ló dé tí eniyan burúkú fi ń kẹ́gàn Ọlọrun,tí ó ń sọ lọ́kàn rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò ní bi mí?”

14. Ṣugbọn ìwọ Ọlọrun rí gbogbo nǹkan,nítòótọ́, o kíyèsí ìṣòro ati ìyà,kí o baà lè fi ọwọ́ ara rẹ gbẹ̀san;nítorí ìwọ ni àwọn aláìṣẹ̀ gbẹ́kẹ̀lé,ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìníbaba.

15. Ṣẹ́ eniyan burúkú ati aṣebi lápá,tú àṣírí gbogbo ìwà burúkú rẹ̀,má sì jẹ́ kí ọ̀kan ninu wọn farasin.

16. OLUWA ni ọba lae ati laelae.Àwọn orílẹ̀-èdè yóo pòórá lórí ilẹ̀ rẹ.

17. OLUWA, o óo gbọ́ igbe àwọn tí a nilára;o óo mú wọn lọ́kàn le,o óo sì dẹ etí sílẹ̀ sí igbe wọn

18. kí o lè ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn aláìníbabaati àwọn ẹni tí à ń pọ́n lójú,kí ọmọ eniyan, erùpẹ̀ lásánlàsàn, má lè dẹ́rù bani mọ́.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 10