Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 33:5-18 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi, wọ́n lọ pàgọ́ sí Sukotu.

6. Wọ́n kúrò ní Sukotu, wọ́n lọ pàgọ́ sí Etamu tí ó wà létí aṣálẹ̀.

7. Láti ibẹ̀ wọ́n pada sẹ́yìn lọ sí Pi Hahirotu tí ó wà níwájú Baali Sefoni, wọ́n pàgọ́ siwaju Migidoli.

8. Wọ́n kúrò níwájú Pi Hahirotu, wọ́n la ààrin òkun kọjá lọ sinu aṣálẹ̀. Lẹ́yìn ìrìn ọjọ́ mẹta ninu aṣálẹ̀ Etamu, wọ́n pàgọ́ sí Mara.

9. Wọ́n kúrò ní Mara, wọ́n lọ pàgọ́ sí Elimu níbi tí orísun omi mejila ati aadọrin igi ọ̀pẹ wà.

10. Wọ́n kúrò ní Elimu, wọ́n lọ pàgọ́ sí etí Òkun Pupa.

11. Wọ́n kúrò níbẹ̀, wọ́n lọ pàgọ́ sí aṣálẹ̀ Sini.

12. Wọ́n kúrò ní aṣálẹ̀ Sini, wọ́n lọ pàgọ́ sí Dofika.

13. Wọ́n kúrò ní Dofika, wọ́n lọ pàgọ́ sí Aluṣi.

14. Wọ́n kúrò ní Aluṣi, wọ́n lọ pàgọ́ sí Refidimu níbi tí wọn kò ti rí omi mu.

15. Wọ́n kúrò ní Refidimu lọ sí aṣálẹ̀ Sinai.

16. Láti aṣálẹ̀ Sinai wọ́n lọ sí Kiburotu Hataafa.

17. Láti Kiburotu Hataafa wọ́n lọ sí Haserotu.

18. Láti Haserotu wọ́n lọ sí Ritima.

Ka pipe ipin Nọmba 33