Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 33:39-51 BIBELI MIMỌ (BM)

39. Aaroni jẹ́ ẹni ọdún mẹtalelọgọfa (123) nígbà tí ó kú ní Òkè Hori.

40. Ọba ìlú Aradi, ní ilẹ̀ Kenaani, tí ń gbé Nẹgẹbu gbúròó pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.

41. Wọ́n kúrò ní Òkè Hori wọn lọ sí Salimona.

42. Wọ́n kúrò ní Salimona wọ́n lọ sí Punoni.

43. Láti Punoni wọ́n lọ sí Obotu.

44. Láti Obotu wọ́n lọ sí Òkè Abarimu ní agbègbè Moabu.

45. Láti Iyimu wọ́n lọ sí Diboni Gadi.

46. Láti Diboni Gadi wọ́n lọ sí Alimoni Dibilataimu.

47. Láti Alimoni Dibilataimu wọ́n lọ sí Òkè Abarimu níwájú Nebo.

48. Láti Òkè Abarimu wọ́n lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jọdani létí Jẹriko.

49. Wọ́n sì pàgọ́ wọn sí ẹ̀bá odò Jọdani láti Beti Jeṣimotu títí dé Abeli Ṣitimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu.

50. OLUWA sọ fún Mose ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jọdani létí Jẹriko pé

51. kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ bá ré odò Jọdani kọjá sí ilẹ̀ Kenaani,

Ka pipe ipin Nọmba 33