Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 24:20-24 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Nígbà tí ó wo Amaleki, ó fi òwe sọ̀rọ̀ nípa wọn báyìí pé:“Amaleki ni orílẹ̀-èdè tí ó lágbára jùlọ,Ṣugbọn yóo ṣègbé níkẹyìn.”

21. Nígbà tí ó wo àwọn ará Keni, ó fi òwe sọ̀rọ̀ nípa wọn báyìí pé:“Ibi ìpamọ́ tí ẹ̀ ń gbédàbí ìtẹ́ tí ó wà lórí àpáta gíga.

22. Ṣugbọn ẹ̀yin ará Keni yóo di ẹni ìparun,àwọn ará Aṣuri yóo ko yín lẹ́rú.”

23. Balaamu tún fi òwe sọ ọ̀rọ̀ wọnyi:“Ta ni yóo là nígbà tí Ọlọrun bá ṣe nǹkan wọnyi?

24. Àwọn ọkọ̀ ojú omi tí wọ́n kún fún ọmọ ogun yóo wá láti Kitimu,wọn yóo borí àwọn ará Aṣuri ati Eberi,ṣugbọn Kitimu pàápàá yóo ṣègbé.”

Ka pipe ipin Nọmba 24