18. Yóo ṣẹgun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ní Edomu,yóo sì gba ilẹ̀ wọn.Yóo ṣẹgun àwọn ará Seiri tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá wọn,yóo sì gba ilẹ̀ wọn.Israẹli yóo sì máa pọ̀ sí i ní agbára.
19. Láti inú ìdílé Jakọbu ni àṣẹ ọba yóo ti jáde wá,yóo sì pa àwọn tí ó kù ninu ìlú náà run.”
20. Nígbà tí ó wo Amaleki, ó fi òwe sọ̀rọ̀ nípa wọn báyìí pé:“Amaleki ni orílẹ̀-èdè tí ó lágbára jùlọ,Ṣugbọn yóo ṣègbé níkẹyìn.”
21. Nígbà tí ó wo àwọn ará Keni, ó fi òwe sọ̀rọ̀ nípa wọn báyìí pé:“Ibi ìpamọ́ tí ẹ̀ ń gbédàbí ìtẹ́ tí ó wà lórí àpáta gíga.
22. Ṣugbọn ẹ̀yin ará Keni yóo di ẹni ìparun,àwọn ará Aṣuri yóo ko yín lẹ́rú.”