Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 24:18-22 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Yóo ṣẹgun àwọn ọ̀tá rẹ̀ ní Edomu,yóo sì gba ilẹ̀ wọn.Yóo ṣẹgun àwọn ará Seiri tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá wọn,yóo sì gba ilẹ̀ wọn.Israẹli yóo sì máa pọ̀ sí i ní agbára.

19. Láti inú ìdílé Jakọbu ni àṣẹ ọba yóo ti jáde wá,yóo sì pa àwọn tí ó kù ninu ìlú náà run.”

20. Nígbà tí ó wo Amaleki, ó fi òwe sọ̀rọ̀ nípa wọn báyìí pé:“Amaleki ni orílẹ̀-èdè tí ó lágbára jùlọ,Ṣugbọn yóo ṣègbé níkẹyìn.”

21. Nígbà tí ó wo àwọn ará Keni, ó fi òwe sọ̀rọ̀ nípa wọn báyìí pé:“Ibi ìpamọ́ tí ẹ̀ ń gbédàbí ìtẹ́ tí ó wà lórí àpáta gíga.

22. Ṣugbọn ẹ̀yin ará Keni yóo di ẹni ìparun,àwọn ará Aṣuri yóo ko yín lẹ́rú.”

Ka pipe ipin Nọmba 24