Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 24:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí Balaamu rí i pé OLUWA ń súre fún àwọn ọmọ Israẹli, kò lọ bíi ti iṣaaju láti bá OLUWA pàdé. Ṣugbọn ó kọjú sí aṣálẹ̀,

2. ó sì rí i bí àwọn ọmọ Israẹli ti pa àgọ́ wọn, olukuluku ẹ̀yà ni ààyè tirẹ̀. Ẹ̀mí Ọlọrun sì bà lé e,

3. ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fi òwe sọ̀rọ̀, ó ní,“Ọ̀rọ̀ Balaamu ọmọ Beori nìyí,ọ̀rọ̀ ẹni tí ó ríran dájúdájú;

4. ìran ẹni tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,mo sì lajú sílẹ̀ kedere rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olodumare.Nítòótọ́ ó ṣubú, ṣugbọn ojú rẹ̀ wà ní ṣíṣí sílẹ̀.

Ka pipe ipin Nọmba 24