Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 23:23-30 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Kò sí òògùn kan tí ó lè ran Jakọbu,bẹ́ẹ̀ ni àfọ̀ṣẹ kan kò lè ran Israẹli.Wò ó! Àwọn eniyan yóo máa wí nípa Israẹli pé,‘Wo ohun tí Ọlọrun ṣe!’

24. Wo orílẹ̀-èdè Israẹli! Ó dìde dúró bí abo kinniun,ó sì gbé ara rẹ̀ sókè bíi kinniun.Kò ní sinmi títí yóo fi jẹ ẹran tí ó pa tán,tí yóo sì fi mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ tán.”

25. Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Níwọ̀n ìgbà tí o ti kọ̀, tí o kò ṣépè lé wọ́n, má súre fún wọn.”

26. Balaamu dá a lóhùn pé, “Ǹjẹ́ n kò tí sọ fún ọ pé ohun tí OLUWA bá sọ fún mi ni mo gbọdọ̀ sọ?”

27. Balaki sọ fún Balaamu pé, “N óo mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá Ọlọrun yóo gbà pé kí o bá mi ṣépè lé àwọn eniyan náà níbẹ̀.”

28. Ó bá mú Balaamu lọ sórí òkè Peori tí ó kọjú sí aṣálẹ̀.

29. Balaamu sọ fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ ìrúbọ meje kí o sì mú akọ mààlúù meje ati àgbò meje wá.”

30. Balaki ṣe ohun tí Balaamu sọ, ó sì fi akọ mààlúù kọ̀ọ̀kan ati àgbò kọ̀ọ̀kan rúbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

Ka pipe ipin Nọmba 23