Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọmba 23:18-29 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Balaamu bá bẹ̀rẹ̀ sí fi òwe sọ̀rọ̀, ó ní:“Balaki, dìde, wá gbọ́,fetí sí mi, ọmọ Sipori;

19. Ọlọrun kò jọ eniyan tí máa ń purọ́,bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe eniyan tí máa ń yí ọkàn pada.Ohun tí ó bá ti sọ ni yóo ṣe,bí ó bá sì sọ̀rọ̀ yóo rí bẹ́ẹ̀.

20. OLUWA ti sọ fún mi pé kí n bukun wọn,Ọlọrun pàápàá ti bukun wọn, èmi kò lè mú ibukun náà kúrò.

21. Kò rí ìparun ninu Jakọbu,bẹ́ẹ̀ ni kò rí ìpọ́njú níwájú Israẹli.OLUWA Ọlọrun wọn wà pẹlu wọn,Òun sì ni ọba wọn.

22. OLUWA mú wọn jáde láti Ijipti wá,Ó sì ń jà fún wọn bí àgbáǹréré.

23. Kò sí òògùn kan tí ó lè ran Jakọbu,bẹ́ẹ̀ ni àfọ̀ṣẹ kan kò lè ran Israẹli.Wò ó! Àwọn eniyan yóo máa wí nípa Israẹli pé,‘Wo ohun tí Ọlọrun ṣe!’

24. Wo orílẹ̀-èdè Israẹli! Ó dìde dúró bí abo kinniun,ó sì gbé ara rẹ̀ sókè bíi kinniun.Kò ní sinmi títí yóo fi jẹ ẹran tí ó pa tán,tí yóo sì fi mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ tán.”

25. Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Níwọ̀n ìgbà tí o ti kọ̀, tí o kò ṣépè lé wọ́n, má súre fún wọn.”

26. Balaamu dá a lóhùn pé, “Ǹjẹ́ n kò tí sọ fún ọ pé ohun tí OLUWA bá sọ fún mi ni mo gbọdọ̀ sọ?”

27. Balaki sọ fún Balaamu pé, “N óo mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá Ọlọrun yóo gbà pé kí o bá mi ṣépè lé àwọn eniyan náà níbẹ̀.”

28. Ó bá mú Balaamu lọ sórí òkè Peori tí ó kọjú sí aṣálẹ̀.

29. Balaamu sọ fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ ìrúbọ meje kí o sì mú akọ mààlúù meje ati àgbò meje wá.”

Ka pipe ipin Nọmba 23